Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlohun maa ba a - n pàṣẹ pé ki a gbé ìmọ̀ oun kaakiri, yala o jẹ lati inu Al-Qur’an ni tabi lati inu Sunna, koda ki nkan naa jẹ kekere gẹgẹ bii aayah kan pere lati inu Al-Qur’an tabi Hadiisi kan pere, pẹlu majẹmu pé ki olujiṣẹ naa jẹ́ onimimọ nipa nkan ti ó fẹ́ jiṣẹ rẹ̀, tí ó sì fẹ́ kéde rẹ̀. Lẹyin naa ni Anabi- ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a- ṣalaye pé ko si aburu pẹlu sisọrọ nipa awọn ọmọ Ísírẹ́lì, ati nipa awọn ìsẹ̀lẹ̀ tí ó ṣẹlẹ̀ sí wọn, pẹlu pé kó ṣá ti má tako ofin sharia tiwa. Lẹyin naa, ó wá wa ní isọra kuro nibi píparọ́ mọ́ òun, nitori pé ẹnikẹni tí ó bá mọ̀ọ́mọ̀ parọ mọ oun, kí ó yaa tètè gba aaye kalẹ̀ fun ara rẹ̀ ninu ina.