explain-icon

Àlàyé

Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- n sọ pé ẹni tí ó bá dáàbò bo iyì ọmọ-iya rẹ ti o jẹ Mùsùlùmí lẹ́yìn ti ko jẹ ki wọn bu u tabi ṣe aburú si i, Ọlọhun maa dáàbò bo oun naa kuro nibi ìyà ni Ọjọ́ Àjíǹde.

explain-icon

Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa

  • Kikọ kúrò nibi sísọ ọ̀rọ̀ tàbùkù iyì àwọn Musulumi.
  • Ẹsan maa wa latara ìran iṣẹ, ẹni ti o ba dáàbò bo iyì ọmọ-ìyá rẹ, Ọlọhun maa dáàbò bo oun naa kuro nibi iná.
  • Isilaamu jẹ ẹsin mímú ara ẹni ni ọmọ-iya ati riran ara ẹni lọ́wọ́ láàrin àwọn Musulumi.