Lati ọdọ Al-Miqdam ọmọ Maadi Karib, ki Ọlọhun yọnu si i, o gba a wa lati ọdọ Anabi, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, o sọ pe: “Bí ọkùnrin kan bá nífẹ̀ẹ́ arákùnrin rẹ̀, kí ó sọ fún un pé òun nífẹ̀ẹ́ rẹ̀”.
O ni alaafia - Abu Daud ati Tirmiziy ati Nasaa'iy ni wọn gba a wa nínú al-Kubrọ, ati Ahmad
Anabi, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, n ṣe alaye ọkan lara awọn okunfa ti o lè fun ajọṣepọ ati ifẹ lagbara laarin awọn onigbagbọ ododo, òun naa ni pe ti ẹnikẹni ba nífẹ̀ẹ́ arakunrin rẹ̀, ki o sọ fun un pe oun nífẹ̀ẹ́ rẹ̀.
Lára àwọn àǹfààní hadiisi naa
Ọla ti n bẹ fún ifẹ tó mọ́ kangá fun Ọlọhun Ọba Aleke ọla, tí kìí ṣe ifẹ nitori anfaani aye.
A fẹ ki a maa sọ fún ẹniti a nifẹẹ nitori Ọlọhun pé a nifẹẹ rẹ̀, kí ifẹ ati irẹpọ le maa lekun si.
Ìtànkálẹ̀ ifẹ laarin awọn onigbagbọ ododo maa n fún ìjẹ́ ọmọ iya ninu ẹsin lagbara ni, ó sì maa n dáàbò bo awujọ kuro nibi tútúká ati pinpin yẹlẹyẹlẹ.