Wọn maa bi olugbagbọ leere ninu saare, awọn mọlaika meji ti a fi ṣe amojuto ìyẹn maa beere lọwọ rẹ nipa ìyẹn, awọn mejeeji ni Munkar ati Nakeer, gẹgẹ bi orúkọ awọn mejeeji ṣe wa ninu ọ̀pọ̀lọpọ̀ awọn hadiisi, O maa jẹrii pe ko si ẹnikan ti ijọsin tọ si afi Allahu ati pe dajudaju Muhammad ojiṣẹ Ọlọhun ni, Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pe eleyii ni ọrọ ti o fi ẹsẹ rinlẹ ti Ọlọhun sọ nipa rẹ pé: (Allāhu yóò máa fi àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo rinlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ t’ó rinlẹ̀ nínú ìṣẹ̀mí ayé àti ní Ọjọ́ Ìkẹ́yìn (Ibrahim, Ayah 27).