Ojiṣẹ Ọlọhun – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – royin pe: Dajudaju iwọ ti wọn kanpa mọ lori gbogbo Musulumi ti o ti balaga ti o ni laakaye ni ki o wẹ ni ọjọ kan ninu gbogbo ọjọ meje inu ọsẹ, nitori naa yio wẹ ni ọjọ yii ori rẹ ati ara rẹ, lati fi wa imọra ati imọtoto, ati pe eyi ti o lọla ju ninu awọn ọjọ yii ni ọjọ jimọ, gẹgẹ bi wọn ṣe gbọ ọ ye ninu awọn ẹgbawa miran, ati pe wiwẹ ni ọjọ jimọ siwaju irun, nkan ti wọn fẹ (sunnah) ni ti fifẹ ti wọn kanpa mọ ni, koda ki o wẹ ni ọjọ alaamisi fun apẹrẹ, ati pe nkan ti o gbe ijẹ dandan yẹn kuro ni gbolohun ‘Aisha – ki Ọlọhun yọnu si i – pe: “Awọn eeyan jẹ oṣiṣẹ ara wọn, wọn si tun jẹ ẹni ti o ṣe pe ti wọn ba lọ fun jimọ wọn yio lọ pẹlu irisi wọn: Ni wọn wa sọ fun wọn pe: Ẹẹ ba si wa wẹ”, Bukhari lo gba a wa, ati pe ninu ẹgbawa miran fun un (Bukhari): “Wọn ni awọn oorun” iyẹn ni pe oorun oogun ati nkan ti o jọ ọ, pẹlu bẹẹ wọn sọ fun wọn pe: “Ẹẹ ba si wẹ”, nitori naa ẹni ti o yatọ si wọn lo wa ni ipo ki o ṣe e (Iwẹ) ju awọn lọ.